Ìfoju tíọ́rì ìṣègbèfábó ti àwọn onímàkísì wo akitiyan akọnibìnrin olúfúnmiláyọ̀ ransome-kútì, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe hàn nínú fíìmù àgbéléwò funmilayo ransome-kútì

A teoria marxista da ação examina os esforços da heroína Funmilayo Ransome-Kutì, conforme mostrado no filme Funmilayo Ransome-Kutì.

Autores/as

  • Taofiq SA’ADU Obafemi Awolowo University -Nigeria https://orcid.org/0009-0000-1708-2805
  • Raphaem Ayo ADESUYAN Adeyemi Federal University of Education -Nigeria
  • Funmilayo Temitope AJÀYÍ Adeyemi Federal University of Education, Ondo, Ondo State, Nigeria

Palabras clave:

Ìjìjàgbara, Ìrẹ́nijẹ, Owó-orí, Awon Obìnrin Ègbá, ìjọba amúnisìn

Resumen

Àfojúsùn ìwádìí yìí ni fífi tíọ́rì ìṣègèfábó ti àwọn Onímàkísì (Marxist Feminism Theory) wo akitiyan akọnibìnrin Olúfúnmiláyọ̀ Ransome-Kuti, nínú ìjìjàgbara owó-orí fún àwọn obìnrin Ẹ̀gbá, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe hàn nínú fíìmù àgbéléwò Funmilayo Ransome-kuti, tí Bolanle Austen-Peters ṣe. Àiuykíyèsí fihàn pé ọ̀pọ̀ ìwádìí tó wà nílẹ̀ nípa tíọ́rì ìṣègbèfábo àti ìsàtakò amúnisìn kò fi bẹ́ẹ̀ kọ ibi ara sí akitiyan àwọn obìnrin nínú ìjìjàgbara fún ẹ̀tọ́ wọn lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe jẹyọ nínú fíìmù àgbéléwò, èyí sì jẹ́ kí àlàfo pàtàkì tí ìwádìí yìí fẹ́ dí. Nítorí náà, nípa ṣíṣe àgbéyẹ̀wò akitiyan àwọn akọnibìnrin tí Olúfúnmiláyọ̀ Rasome-Kútì jẹ́ olórí fún àti ìbáṣepọ̀ agbára òṣèlú nínú ìjijàgbara ìsàtakò sí ìrẹ́nijẹ, ìtẹnimẹ́rẹ̀ àti ìfipágbowó-orí lọ́wọ́ ẹni láti ọwọ́ àwọn ìjọ̀ba amúnisìn a ó lè rí ohun tuntun fi kún ìmọ̀. Ọgbọ́n ìṣèwádìí méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni iṣẹ́ yìí ṣe àmúlò. Àkọ́kọ́ ni ṣíṣe àkójọpọ̀ ọ̀kan-ò-jọ̀kan ọ̀gangan-ipò ibi tí wọ́n ti ṣe àmúlò irinṣẹ́ ìṣègbèfábo àti ìsàtakò ìmúnisìn nínú fíìmù Fúnmiláyọ Ransome-Kúti.  Ìlànà ìwádìí kejì ni ṣíse àmúlò àwọn àpilẹ̀kọ tó wúlò fún ìwádìí yìí. Àwọn bí; ìwé, Jọ́nà, àkọsílẹ̀ ìtàn, àti àwọn ìwé lórí Íńtánẹ́ẹ̀tì tó jẹ mọ́ ìṣègbèfábo ti àwọn Onímáàkísì, ìjìjàgbara àwọn obìnrin Nàìjíríà, àti ìtàn ìjọba amúnisìn. Àwọn àkójọ-èdè-fáyẹ̀wò yìí ni a fi tíọ́rì ìṣègbèfábo ti àwọn Onímáàkísì ṣe ìtúpalẹ̀. Àbájáde ìwádìí yìí fi hàn pé àgbékalẹ̀ fíìmù yìí mú, wá sí ìrántí, akitiyan akọni-bìnrin Olúfúnmiláyọ̀ Rasome-Kútì àti ipa àwọn obìnrin nípa ìjìjàgbara owó-orí fún àwọn obìnrin Ẹ̀gbá lábẹ́ ìjọba amúnisìn. Bákan náà, ó tún fi hàn pé ìfọwọ́sowọ́pọ̀ àwọn obìnrin jẹ ọ̀nà kan tí wọ́n fi lè gba ara wọn sílẹ̀ lọ́wọ́ ìjẹgàba àwọn ọkùnrin tí wọ́n ń mú wọn sìn. Ìwádìí yìí fi kún ìmọ̀ nípa àyẹ̀wò fíìmù Yorùbá tó dá lórí ipa àti ipò àwọn obìnrin ní àwùjọ. Ó tún ran àgbóyé nípa àwọn ìtúmọ̀ tí ó fara sin nípa ìjàjàgbara lọ́wọ́. Iṣẹ́ yìí tún fi kún ìmọ̀ nípa síso ìṣègbèfábo àwọn Onímáàkísì pọ̀ mọ́ àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ inú fíìmù Nàìjíríà, tí ó ń gbé ọ̀rọ̀ lórí dídáàbò bo ẹ̀tọ́ àwọn obìnrin nínú sinimá ilẹ̀ Adúláwọ̀ ga.

**********

O objetivo deste estudo é examinar os esforços da heroína Olufunmilaye Ransome-Kuti, na luta pelos direitos das mulheres em Egba, conforme retratado no documentário Funmilayo Ransome-kuti, dirigido por Bolanle Austen-Peters, utilizando a Teoria do Feminismo Marxista. É importante notar que a maioria dos estudos existentes sobre a teoria do feminismo e do anticolonialismo não tem dado muita atenção aos esforços das mulheres na luta por seus direitos contra os homens, como retratado no documentário, o que deixa uma lacuna importante que este estudo visa preencher. Portanto, ao examinar os esforços das heroínas lideradas por Olufunmilek Ransome-Kuti e a relação entre o poder político na luta contra a opressão, a exploração e a extorsão por governos coloniais, podemos encontrar algo novo para adicionar ao nosso conhecimento. Este trabalho utiliza duas estratégias de pesquisa diferentes. A primeira é compilar um conjunto abrangente de situações em que as ferramentas de resistência e de resistência ao colonialismo são utilizadas no filme Funmilayo Ransome-Kuti. A segunda estratégia de pesquisa consiste em utilizar artigos relevantes para este estudo, como livros, periódicos, documentos históricos e recursos online relacionados ao ativismo marxista, às lutas das mulheres nigerianas e à história colonial. Esses textos foram analisados ​​sob a perspectiva da teoria do ativismo marxista. Os resultados deste estudo demonstram que o cenário do filme evoca os esforços heroicos da protagonista Olufunmilek Rasome-Kutì e o papel das mulheres na luta tributária das mulheres Egba sob o domínio colonial. Mostra também que a participação feminina é uma forma de libertação da dominação masculina opressora. Esta pesquisa contribui para o conhecimento da análise do cinema iorubá, com foco no papel e na condição da mulher na sociedade. Auxilia ainda na compreensão dos significados ocultos da luta. Este trabalho também contribui para o entendimento da relação entre a resistência marxista e os eventos presentes no cinema nigeriano, levantando a questão da proteção dos direitos das mulheres no cinema negro.

Descargas

Los datos de descargas todavía no están disponibles.

Biografía del autor/a

Taofiq SA’ADU, Obafemi Awolowo University -Nigeria

tí ó kẹ́kọ̀ọ́ gboyè Ph.D. nínú Èdè àti Lítírésọ̀ Yorùbá, láti YunifásítìỌbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ tí ilẹ́-Ifẹ̀ ní Orílẹ̀ èdè Nàí́jíríà, ìwádìí rẹ̀ gbájúmọ́ ewì alohùn ajẹmọ́rìṣà Yorùbá láti mú ìgbòòrò bá àwùjọ Yorùbá. Gẹ́gẹ́ bí olùkọ́ni ní Yunifásítì Olùkọ́ni tí Ìjọba Àpapọ̀ ní Adeyemi, Òǹdó, àti igbákejì adarí fún ẹ̀ka ẹ̀kọ́ gíga, ó so ọgbọ́n ìjìnlẹ̀ Yorùbá pọ̀ mọ́ ìmọ̀ ìwádìí òde òní. Pẹ̀lú irírí tí ó lé ní ogún ọdún nínú ìgbóhùn-sáfẹ́fẹ́, ó máa ń yí àwọn ìtàn àròsọ Yorùbá sí àwọn ètò tí ó rọrùn láti gbọ́ àti láti wò, báyìí ló ṣe ń gbé àṣà lárugẹ.

Raphaem Ayo ADESUYAN , Adeyemi Federal University of Education -Nigeria

jẹ́ ọ̀jọ̀gbọ́n èdè àti Lítíréṣọ̀ Yorùbá ní Ẹ̀ka-ẹ̀kọ́ èdè Yorùbá ní Àdéyẹmí Yunifásítì Olùkọ́ni tí Ìjọba Àpapọ̀ ní Ọ̀ndó, Ìpínlẹ̀ Ọ̀ndó, ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó lọ sí Ilé-ẹ̀kọ́ gíga Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ Yunifásítì fún oyè-ẹ̀kọ́ Bí-Eè, Ẹ́m-Eè àti oyè ìjìnlẹ̀ gíga nínú èdè àti Lítíréṣọ̀ Yorùbá. Ó tún lọ sí Ilé-ẹ̀kọ́ gíga Yunifásítì Ìlọrin, Ìlọrin, Ìpínlẹ̀ Kwara, Nàìjíríà fún oyè-ẹ̀kọ́ Ẹ́m-Eè nínú èdè Yorùbá. Àfojúsùn ìkọ́ni, iṣẹ́ ìwádìí àti àtẹ̀jáde rẹ̀ lórí èdè àti Lítíréṣọ̀ Yorùbá jẹ́ mọ́ Síntáàsì àti Ẹ̀ka-èdè. Ó ti ṣe àtẹ̀jáde àwọn ìwé méjì (àgbéyẹ̀wò Síntáàsì èdè Yorùbá) àti àtẹ̀jáde ogójì àtíkù nínú àwọn gbajúmọ̀ ìwé àti jọ́nà ní Nàìjíríà àti lókè-òkun, bíi “Ẹ̀kọ́ ìjìnlẹ̀ fún Àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ àti Olùkọ́”, CROFEX, OJÚ-ÌWÉ 27–35. Ó jẹ́ olóòtú agbà fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwé àti jọ́nà (ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú iṣẹ́ Adébáyọ̀ Fálétì àti Ìtànṣán Ọ̀ọ̀duà (jọ́nà ẹgbẹ́ olùkọ́ èdè Yorùbá). Ó ti kópa nínú àpérò ní Nàìjíríà àti ní òkè-òkun. Ó jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ Onímọ̀ èdè Yorùbá, Nàìjíríà, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Iṣẹ́ ìwádìí rẹ̀ tó ń lọ lọ́wọ́lọ́wọ́ jẹ́ mọ́ àgbéyẹ̀wò àwọn ọ̀rọ̀-onítumọ̀ girama ní àwọn ẹ̀ka-èdè Yorùbá ìlà-oòrùn.

Funmilayo Temitope AJÀYÍ , Adeyemi Federal University of Education, Ondo, Ondo State, Nigeria

jẹ́ Olùkọ́ni Àgbà ní Ẹ̀ka-Ẹ̀kọ́ Èdè Yorùbá, ní Yunifásítì Olùkọ́ni tí Ìjọba Àpapọ̀ ní Adeyemi, Òǹdó, ní Orílẹ̀ èdè Nàí́jíríà. Ó gba oyè ìmọ̀-ìjìnlẹ̀ nínú Lítírésọ̀ Yorùbá láti Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ University, Ilé-Ifẹ̀. Ìwádìí rẹ̀ dá lé ojú-àmúwayé Yorùbá, ìmọ̀ ìjìnlẹ̀-èrò Yorùbá àti ètò ìgbàgbọ́ Yorùbá nípa àṣàyàn ẹranko nínú àwọn ẹ̀ka lítírésọ̀ alohùn bíi oríkì, ìjàlá, ìrẹmọjẹ, àti ẹ̀sẹ̀ Ifá. Ìwádìí Ọ̀mọ̀wé Àjàyí ṣàlàyé àwọn ìpèníjà òde-òní bíi ìdàgbàsókè láwùjọ, dídọ́gba  takọ-tabo, ètò ààbò, àti ìpamọ́ àṣà. 

Citas

Adebayo, S. (2021). The rise of female producers in the New Nollywood: A feminist perspective. Nigerian Film Journal, 12(1), 34–50.

Adéoyè, C. L. (1985). Ìgbàgbọ́ àti Ẹ̀sìn Yorùbá. Evans Brothers Nigeria Publishers Ltd.

Adesokan, A. (2021). Postcolonial African cinema: Ten directors. Indiana University Press.

Adoga, J. (2019). Funmilayo Ransome-Kuti (Nigeria Heritage Children’s Series). +234Express.

Adoga, T. (2015). The Yoruba video film: A socio-political critique. University Press.

Akinsola, I., & Osundiran, E. E. (2025). The erosion of tradition in an age of globalization: Cultural hybridity and marginality in contemporary Yoruba films. NOTION: Journal of Linguistics, Literature, and Culture, 7(2), 349–361. https://doi.org/10.12928/notion.v7i2.12405

Akinyemi, A. (2018). Tunde Kelani's films and the preservation of Yoruba oral traditions. In A. Salami (Ed.), Yoruba Culture and Media. University of Ibadan Press.

Althusser, L. (1971). Lenin and philosophy and other essays. Monthly Review Press.

Asante, E., & Mansah, S. A. (2025). The power of women in war and adversity: A dramatic discourse of Duro Ladipo’s Moremi. International Journal on Studies in English Language and Literature (IJSELL), 13(12), 22–28. https://doi.org/10.20431/2347-3134.1312003

Austen-Peters, B. (Director). (2024). Funmilayo Ransome-Kuti [Film]. Bolanle Austen-Peters Productions.

Awe, B. (1992). Nigerian women in historical perspective. Sankore Publishers.

Ayobami, O. (2022). Cinematic evolution: From stage to screen in Yoruba drama. Lagos State University Press.

Barrett, M. (2014). Women's oppression today: The Marxist/Feminist encounter. Verso Books.

Bhattacharya, T. (Ed.). (2017). Social reproduction theory: Remapping class, recentering oppression. Pluto Press.

Byfield, J. A. (2002). The bluest hands: A social and economic history of women dyers in Abeokuta (Nigeria), 1890-1940. Heinemann.

Chuku, G. (2020). Nigerian women in historical perspective. Lagos University Press.

Denzer, L. (1998). The Iyalode in Yoruba politics and administration. Sam Bookman Publishers.

Falola, T. (2002). Key events in African history: A reference guide. Greenwood Press.

Federici, S. (2020). Revolution at point zero: Housework, reproduction, and feminist struggle (2nd ed.). PM Press.

Federici, S. (2021). Caliban and the witch: Women, the body and primitive accumulation. Autonomedia.

Ferguson, S. (2019). Women and work: Feminism and capitalism. Pluto Press.

George, A. (2014). Making modern girls: A history of childhood, city life, and social assistance in colonial Lagos. Ohio University Press.

Hajji, A. B. (2021). Cinematic representations of African female icons. African Arts Journal, 14(2), 112–125.

Hajji, U. M. (2020). Ìtàn Ìgbésí Ayé Chief Mrs. Funmilayo Ransome-Kuti [The life and times of Chief Mrs. Funmilayo Ransome-Kuti] (Yoruba Ajami ed.). Local Publication.

Haynes, J. (2016). Nollywood: The creation of Nigerian film genres. University of Chicago Press.

Johnson-Odim, C., & Mba, N. E. (1997). For women and the nation: Funmilayo Ransome-Kuti of Nigeria. University of Illinois Press.

Kehinde, F. (n.d.). A short stroll along history avenue (Chapter 6). [Self-Published/Local Press].

Lawuyi, O. B. (2021). The depersonalized as vanishing hero and heroine in Yorùbá moral placards. Yoruba Studies Review, 3(1), 1–21. https://doi.org/10.32473/ysr.v3i1.129926

Marx, K., & Engels, F. (1948). The Communist Manifesto (Original work published 1848). International Publishers.

Mba, N. E. (1982). Nigerian women mobilized: Women's political activity in Southern Nigeria, 1900-1965. University of California Press.

Ogunleye, F. (2023). African video movies and the oral tradition: A study in aesthetics and social impact. Academic Press.

Oladiti, A. A. (2013). The dynamics of market women in the socio-economic development of colonial Abeokuta. Journal of Culture, Society and Development, 1, 45–56.

Olajubu, O. (2003). Women in the Yoruba Religious Sphere. State University of New York Press.

Olasope, K. (2023). Historical narratives and contemporary Nigerian cinema: A study of Kunle Afolayan and Bolanle Austen-Peters. Journal of African Cultural Studies, 15(4), 201–218.

Onajin, A., & Ofoego, C. (2020). Narrative techniques in Bolanle Austen-Peters' productions. Journal of Film and Media Studies, 8(1), 45–60.

Onajin, A., & Ofoego, O. (with Falola, T.). (2015). Funmilayo Ransome-Kuti and the Women’s Union of Abeokuta. UNESCO Publishing.

Oyěwùmí, O. (1997). The Invention of Women: Making an African Sense of Western Gender Discourses. University of Minnesota Press.

Oyěwùmí, O. (2000). Family bonds/conceptual binds: African notes on feminist epistemologies. Signs: Journal of Women in Culture and Society, 25(4), 1093–1098. https://doi.org/10.1086/495529

Oyibo, E. (2018). Historical films and the preservation of Yoruba cultural identity. Cultural Studies Review, 22(3), 88–102.

Oyibo, O., & Adoga, J. (2020). Funmilayo Ransome-Kuti: An inspiring history storybook for kids. People’s Activist Series.

Panata, S. (2022). Funmilayo Ransome-Kuti and the 1947–1948 Abeokuta women’s protest: New perspectives on a landmark event. Journal of African History, 63(1), 89–105.

Salami, Y. K. (2018). Yoruba culture and social dynamics. University of Lagos Press.

Sanda, A. O. (2011). The Sociology of African Literature. Spectrum Books.

Sesan, A. A. (2025). Towards a renaissance of Yoruba (indigenous) language and culture in the new cinematic mode in Nigeria. Journal of African Cinemas, 17(3), 227–240. https://doi.org/10.1386/jac_00152_1

Steady, F. C. (2005). African women: Theoretical and practical considerations. Schenkman Books.

Vaughan, O. (2000). Nigerian chiefs: Traditional power in modern politics, 1890s-1990s. University of Rochester Press.

Vogel, L. (2013). Marxism and the Oppression of Women: Toward a Unitary Theory. Haymarket Books.

Publicado

27-08-2026

Cómo citar

SA’ADU, T., ADESUYAN , R. A., & AJÀYÍ F. T. (2026). Ìfoju tíọ́rì ìṣègbèfábó ti àwọn onímàkísì wo akitiyan akọnibìnrin olúfúnmiláyọ̀ ransome-kútì, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe hàn nínú fíìmù àgbéléwò funmilayo ransome-kútì: A teoria marxista da ação examina os esforços da heroína Funmilayo Ransome-Kutì, conforme mostrado no filme Funmilayo Ransome-Kutì. NJINGA&SEPÉ: evista nternacional e ulturas, Línguas fricanas rasileiras, 6(Especial II), 249–267. ecuperado a partir de https://revistas.unilab.edu.br/njingaesape/article/view/2921